Yoruba Paper 2 WASSCE (SC), 2020

Question 7

 

Ṣàlàyé mẹ́fà nínú àwọn  kókó tí ó sú yọ nínú oríkì “Ìran Ọlọ́fà”.


This oral poetry question was based on the eulogy of the Ọlọ́fà lineage.

Àwọn kókó tí ó sú yọ nínú oríkì Ìran Ọlọ́fà (Mú mẹ́fà nínú wọn)

  1. Ọlálọmí jẹ ọba ìlú Ọ̀fà lẹ́yìn tí ó borí ìjòyè mẹ́fà nínu ìjàkadì.
  2. Tápà ni ìyá Ọlọ́fà, Yánrin sì ni orúkọ rẹ̀ ní èdè Tápà.
  3. Wọn kì í pe ẹ̀fọ́ yánrin lórúkọ; wọ́n ń dà á pè ní látìpá Ọ̀ṣun/látìpá
  4. Ìjàkadì ni orò wọn.
  5. Àwọn ni wọ́n ń kì ní ìran Ọlọ́fàmọjọ̀, ìyẹ̀rú ọ̀kín, ọmọ abíṣujóókọ.
  6. Wọ́n jẹ́ jagunjagun.
  7. Ọ̀kan nínú àwọn aya Ọlálọmí lóyún nígbà tí Ọlálọmi lọ sójú ogun.
  8. Wọ́n pe oríṣiríṣi ènìyàn láti lọ mú àgbàdo wá fún ẹṣin ọba ní abẹ́ àká.
  9. Gbogbo wọn kọ̀ wọn ò lọ.
  10. Ìyàwó tó lóyún yìí ni ó lọ sí abẹ́ àká láti lọ mú àgbàdo.
  11. Ìyàwó náà bímọ sí abẹ́ àká.
  12. Wọ́n wá ọmọ Ọlọ́fà tí yóò lọ kó ọmọ wá sílé wọn ò rí
  13. Ìwọ̀fà ọba ló lọ kó ọmọ wá sílé
  14. Nígbà tí Ọlọ́fà padà tí ojú ogun dé, wọ́n ròyìn fún un.
  15. Ó wá gégùn-ún pé ègún ẹnu ẹrú ni yóò máa rinlẹ̀ lỌ́fà ju ti ọmọbíbí ilé wọn lọ.
  16. Omi wọ́n ju ọtí lọ ní ilé wọn.
  17. Lórí igi àràbà ni Ìran Ọlọ́fà ti máa ń ṣe orò àṣegbẹ̀yìn fún òkú tí ó bá kú láàrin wọn.
  18. Wọ́n máa ń dá aró láti fi rẹ aṣọ
  19. Oríṣiríṣi ìlù wà ní ààfin Ọlọ́fà tí wọ́n fi máa ń dárayá, b.a. bàtá, aro, abbl.

 

Most candidates showed a lack of knowledge of the prescribed text: Babalọlá’s Àwọn Oríkì Orílẹ̀ Mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n.