Yoruba Paper 2 WASSCE (SC), 2020

Question 11

 

Ṣe àpèjúwe ilé tí  Fẹ́mi ń gbé ní Nàìjíríà.


Candidates were required to describe Fẹ́mi’s house in Nigeria.

Àpèjúwe ilé tí Fẹ́mi ń gbé ní Nàìjíríà:

  1. Ilé-ilẹ̀ ni ilé náà.
  2. Ó tóbi, ó sì lẹ́wà púpọ̀.
  3. Ó ní ilé kékeré lẹ́yìn, tí àwọn òṣìṣẹ́ ń gbé.
  4. Wọ́n to búlọ́ọ̀kù ìgbàlódé tí ó wọnú ara wọn sí ilẹ̀ àyíká ilé náà.
  5. Ilé ìgbọ́kọ̀sí wà ní apá òsì géètì.
  6. Wọ́n gbin oríṣiríṣi arẹwà òdòdó yíká ilé náà.
  7. Ọkọ̀ mẹ́ta ni wọ́n kó sí ibi ìgbọ́kọ̀sí.
  8. Àwo alálẹ̀mọ́lẹ̀(táìlì) ní wọ́n lẹ̀ mọ́ gbogbo ilẹ̀ inú ilé náà.
  9. Gbogbo ohun tí ó wà nínú iyàrá ìgbàlejò ni ó ń dán gbinrin.
  10. Ọ̀dà funfun ni wọ́n fi kun iyàrá ìgbàlejò.
  11. Tìmùtìmù tí wọ́n fi awọ aláwọ̀ oriṣiríṣi ṣe ni ó wà nínú iyàrá náà.
  12. Ẹní àtẹ́ẹ̀ká tí wọ́n ya àmọ̀tẹ́kùn ńlá kan sí wà láàrin iyàrá náà.
  13. Tábìlì onígíláàsì ni wọ́n gbé lé orí ẹní àtẹ́ẹ̀ká náà.
  14. Tẹlifíṣàn ńlá gbàǹgbà pẹlẹbẹ kan ni wọ́n fi kọ́ ara ògiri.
  15. Tábìlì ìjẹun kan wà ní ẹ̀gbẹ́ kan lápá òsì iyàrá náà tí ó ń dán gbinrin.
  16. Ilé ìdáná pàápàá dàbí ẹni pé ìlú òyìnbó ni ènìyàn wà.
  17. Ọ̀pọ̀lọ̀pọ̀ ẹ̀rọ ìgbàlódé ni ó wà nínú ilé náà.

 

Most candidates, who read the prescribed text, gave a proper description of Fẹ́mi’s house in Nigeria and scored good marks.