Yoruba Paper 2 WASSCE (SC), 2022

Question 11

Mẹ́nu ba àwọn ọ̀rọ̀ tí bàbá Àdìó sọ nígbà tí ó para dà di wòlíì.

 

Observation

Candidates were expected to mention the words of Adìó’s father to the other characters when he reappeared as a prophet.

Àwọn ọ̀rọ̀ tí bàbá Àdìó sọ nígbà tí ó para da di wòlíì:

  1. Ó ní ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò níí jẹ́ kí wọ́n mọ ẹni tí ó wá bẹ̀ wọ́n wò
  2. Ó ní wọ́n rí wòlíì wọ́n sì ń pè é ní egúngún
  3. Ó ní òun sọ pé “Alelúyà” àwọn rò pé “Eríwo yà” ni òun wí
  4. Bàbá tún béèrè pé ǹjẹ́ Ọládẹ̀jọ kò ha ṣe ojú kòkòrò sí aya òṣìṣẹ́ rẹ̀?
  5. Bàbá tún béèrè pé kí ló máa ń ṣe àwọn ọmọ ènìyàn tí wọ́n máa ń pa irọ́ ojúkorojú báyìí?
  6. Ó ní tí Ọládẹ̀jọ bá tún purọ́, ilé rẹ̀ yóò jóná kanlẹ̀
  7. Ó ní ṣé ó ṣe tán tí yóò jẹ́wọ́?
  8. Ó ní kí ó fi ẹnu ara rẹ̀ jẹ́wọ́ kí ó sì sọ bí ó ṣe ṣẹlẹ̀ gan-an
  9. Bàbá ní òun ń bọ̀ wá bá Àdíjá; kí Àdíjá má tíì pariwo
  10. Ó sọ fún Ọládẹ̀jọ pé nílé òṣìṣẹ́ rẹ̀ ni ó ti lọ bá aya òṣìṣẹ́ rẹ̀
  11. Ó sọ fún Àdìó pé ó yẹ gbogbo ènìyàn kó dínwó aró, kò ma yẹ atọ̀ọ̀lé
  12. Ó ní ṣèbí bí Ọládẹ̀jọ ṣe wáá ká aya Àdìó mọ́lé ni Àdìó náà ń mú aya Ọládẹ̀jọ lọ sílé?
  13. Lẹ́yìn tí ó para dà tí ó kúrò ní wòlíì, ó ní àṣírí tiwọn ló tú, ó ní ti àwọn kọ́ ló tú
Candidates who attempted the question performed poorly, many of their responses were partially adequate